Jobu 25
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìdáhùn Bilidadi
25 Nígbà náà ní Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn wí pé:
2 “Ìjọba àti ẹ̀rù ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀,
òun ní i ṣe ìlàjà ní ibi gíga gíga ọ̀run.
3 Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí,
tàbí ara ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
4 Èéha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run?
Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?
5 Kíyèsi i, òṣùpá kò sì lè tàn ìmọ́lẹ̀,
àní àwọn ìràwọ̀ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀,
6 kí a má sọ ènìyàn tí i ṣe ìdin,
àti ọmọ ènìyàn tí í ṣe kòkòrò!”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.