Add parallel Print Page Options

Kò sí ọ̀kan tí o jẹ́ olóòtítọ́

“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu
    wò yíká, kí o sì mọ̀,
kí o sì wá kiri
    Bí o bá le è rí ẹnìkan,
tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo,
    n ó dáríjì ìlú yìí.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’
    síbẹ̀ wọ́n búra èké.”

Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́
    Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n.
Ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà.
    Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ,
    wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí;
    wọn jẹ́ aṣiwèrè,
nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa,
    àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ,
    n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀;
ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa
    àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.”
Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́,
    wọ́n sì ti já ìdè.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n,
    ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run,
ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín
    ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
nítorí àìgbọ́ràn yín pọ,
    ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.

“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́?
    Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀
àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra.
    Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn,
síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà
    wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó,
    tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?”
    ni Olúwa wí.
    “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi
    lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?

10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run,
    ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá.
Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò,
    nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda
    ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,”
    ni Olúwa wí.

12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa;
    wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan!
Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá;
    àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́,
    ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn.
    Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”

14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí:

“Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí;
    Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná,
    àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí,
    “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín
Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì
    àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀,
    tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí
    gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ,
    àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin,
wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ,
    wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ.
Pẹ̀lú idà ni wọn ó run
    ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.

18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá. 19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’

20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu,
    kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 (A)Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn,
    tí ó lójú ti kò fi ríran
    tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí.
    “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí?
Mo fi yanrìn pààlà Òkun,
    èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé.
Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀;
    wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀,
    wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé,
    ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa,
ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀,
    tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò,
    ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.

26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà
    tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ,
    àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ,
    ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn.
Wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28     Wọ́n sanra wọ́n sì ń dán.
Ìwà búburú wọn kò sì lópin;
    wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀.
    Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?”
    ni Olúwa wí.
“Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi
    lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?

30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara
    ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké,
    àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn,
àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí,
    kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

Not One Is Upright

“Go up and down(A) the streets of Jerusalem,
    look around and consider,(B)
    search through her squares.
If you can find but one person(C)
    who deals honestly(D) and seeks the truth,
    I will forgive(E) this city.
Although they say, ‘As surely as the Lord lives,’(F)
    still they are swearing falsely.(G)

Lord, do not your eyes(H) look for truth?
    You struck(I) them, but they felt no pain;
    you crushed them, but they refused correction.(J)
They made their faces harder than stone(K)
    and refused to repent.(L)
I thought, “These are only the poor;
    they are foolish,(M)
for they do not know(N) the way of the Lord,
    the requirements of their God.
So I will go to the leaders(O)
    and speak to them;
surely they know the way of the Lord,
    the requirements of their God.”
But with one accord they too had broken off the yoke
    and torn off the bonds.(P)
Therefore a lion from the forest(Q) will attack them,
    a wolf from the desert will ravage(R) them,
a leopard(S) will lie in wait near their towns
    to tear to pieces any who venture out,
for their rebellion is great
    and their backslidings many.(T)

“Why should I forgive you?
    Your children have forsaken me
    and sworn(U) by gods that are not gods.(V)
I supplied all their needs,
    yet they committed adultery(W)
    and thronged to the houses of prostitutes.(X)
They are well-fed, lusty stallions,
    each neighing for another man’s wife.(Y)
Should I not punish them for this?”(Z)
    declares the Lord.
“Should I not avenge(AA) myself
    on such a nation as this?

10 “Go through her vineyards and ravage them,
    but do not destroy them completely.(AB)
Strip off her branches,
    for these people do not belong to the Lord.
11 The people of Israel and the people of Judah
    have been utterly unfaithful(AC) to me,”
declares the Lord.

12 They have lied(AD) about the Lord;
    they said, “He will do nothing!
No harm will come to us;(AE)
    we will never see sword or famine.(AF)
13 The prophets(AG) are but wind(AH)
    and the word is not in them;
    so let what they say be done to them.”

14 Therefore this is what the Lord God Almighty says:

“Because the people have spoken these words,
    I will make my words in your mouth(AI) a fire(AJ)
    and these people the wood it consumes.(AK)
15 People of Israel,” declares the Lord,
    “I am bringing a distant nation(AL) against you—
an ancient and enduring nation,
    a people whose language(AM) you do not know,
    whose speech you do not understand.
16 Their quivers(AN) are like an open grave;
    all of them are mighty warriors.
17 They will devour(AO) your harvests and food,
    devour(AP) your sons and daughters;
they will devour(AQ) your flocks and herds,
    devour your vines and fig trees.(AR)
With the sword(AS) they will destroy
    the fortified cities(AT) in which you trust.(AU)

18 “Yet even in those days,” declares the Lord, “I will not destroy(AV) you completely. 19 And when the people ask,(AW) ‘Why has the Lord our God done all this to us?’ you will tell them, ‘As you have forsaken me and served foreign gods(AX) in your own land, so now you will serve foreigners(AY) in a land not your own.’

20 “Announce this to the descendants of Jacob
    and proclaim(AZ) it in Judah:
21 Hear this, you foolish and senseless people,(BA)
    who have eyes(BB) but do not see,
    who have ears but do not hear:(BC)
22 Should you not fear(BD) me?” declares the Lord.
    “Should you not tremble(BE) in my presence?
I made the sand a boundary for the sea,(BF)
    an everlasting barrier it cannot cross.
The waves may roll, but they cannot prevail;
    they may roar,(BG) but they cannot cross it.
23 But these people have stubborn and rebellious(BH) hearts;
    they have turned aside(BI) and gone away.
24 They do not say to themselves,
    ‘Let us fear(BJ) the Lord our God,
who gives autumn and spring rains(BK) in season,
    who assures us of the regular weeks of harvest.’(BL)
25 Your wrongdoings have kept these away;
    your sins have deprived you of good.(BM)

26 “Among my people are the wicked(BN)
    who lie in wait(BO) like men who snare birds
    and like those who set traps(BP) to catch people.
27 Like cages full of birds,
    their houses are full of deceit;(BQ)
they have become rich(BR) and powerful
28     and have grown fat(BS) and sleek.
Their evil deeds have no limit;
    they do not seek justice.
They do not promote the case of the fatherless;(BT)
    they do not defend the just cause of the poor.(BU)
29 Should I not punish them for this?”
    declares the Lord.
“Should I not avenge(BV) myself
    on such a nation as this?

30 “A horrible(BW) and shocking thing
    has happened in the land:
31 The prophets prophesy lies,(BX)
    the priests(BY) rule by their own authority,
and my people love it this way.
    But what will you do in the end?(BZ)