Add parallel Print Page Options

Ọmọ tí o ṣe pàtàkì fún àwọn Angẹli

Ní ìgbà àtijọ́, Ọlọ́run bá àwọn baba ńlá wa sọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì ní ọ̀pọ̀ ìgbà àti ní onírúurú ọ̀nà, ṣùgbọ́n ní ìgbà ìkẹyìn yìí Ọlọ́run ń bá wa sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi, ẹni tí ó fi ṣe ajogún ohun gbogbo, nípasẹ̀ ẹni tí ó dá gbogbo ayé yìí àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀: Ọmọ tí í ṣe ìtànṣán ògo Ọlọ́run àti àwòrán òun tìkára rẹ̀, tí ó sì ń fi ọ̀rọ̀ agbára rẹ̀ mú ohun gbogbo dúró: Lẹ́yìn tí ó ti ṣe ìwẹ̀nù ẹ̀ṣẹ̀ wa tan, ó wá jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọláńlá ní òkè. Nítorí náà, ó sì ti fi bẹ́ẹ̀ di ẹni tí ó ga ní ipò ju angẹli lọ, bí ó ti jogún orúkọ èyí tí ó tayọ̀ tiwọn.

(A)Nítorí kò sí ọ̀kan nínú àwọn angẹli tí Ọlọ́run fi ìgbà kan sọ fún pé:

“Ìwọ ni ọmọ mi;
    lónìí ni mo bí ọ”?

Àti pẹ̀lú pé;

“Èmi yóò jẹ́ baba fún un,
    Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi”?

(B)Àti pẹ̀lú, nígbà tí Ọlọ́run rán àkọ́bí rẹ̀ wá si ayé wa yìí. Ó pàṣẹ pé,

“Ẹ jẹ́ kí gbogbo àwọn angẹli Ọlọ́run foríbalẹ̀ fún un.”

(C)Àti nípa ti àwọn angẹli, ó wí pé;

“Ẹni tí ó dá àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀mí,
    àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”

(D)Ṣùgbọ́n ó sọ nípa tí Ọmọ rẹ̀ pé,

“Ìtẹ́ rẹ, Ọlọ́run, láé àti láéláé ni,
    ọ̀pá aládé òdodo ni ọ̀pá ìjọba rẹ.
Ìwọ fẹ́ òdodo, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kórìíra iṣẹ́ búburú;
nítorí èyí ni Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ ṣe fi ààmì òróró ayọ̀ yàn ọ
    tí ó gbé ọ ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”

10 Ó tún sọ pé,

“Ní àtètèkọ́ṣe, ìwọ Olúwa, ìwọ fi ìdí ayé sọlẹ̀,
    àwọn ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ.
11 Wọn yóò ṣègbé, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà síbẹ̀
    gbogbo wọn ni yóò di àkísà bí ẹ̀wù.
12 Ní kíká ni ìwọ yóò ká wọn bí aṣọ,
    bí ìpààrọ̀ aṣọ ni a ó sì pààrọ̀ wọn.
Ṣùgbọ́n ìwọ fúnrarẹ̀ kì yóò yípadà
    àti pé ọdún rẹ kì yóò ní òpin.”

13 (E)Èwo nínú àwọn angẹli ní a gbọ́ pé Ọlọ́run fi ìgbà kan wí fún pé,

“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
    títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ
    di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ”?

14 Kì í ha á ṣe ẹ̀mí tí ń jíṣẹ́ ni àwọn angẹli í ṣe bí; tí a rán lọ síta láti máa ṣiṣẹ́ fún àwọn tí yóò jogún ìgbàlà?

God’s Final Word: His Son

In the past God spoke(A) to our ancestors through the prophets(B) at many times and in various ways,(C) but in these last days(D) he has spoken to us by his Son,(E) whom he appointed heir(F) of all things, and through whom(G) also he made the universe.(H) The Son is the radiance of God’s glory(I) and the exact representation of his being,(J) sustaining all things(K) by his powerful word. After he had provided purification for sins,(L) he sat down at the right hand of the Majesty in heaven.(M) So he became as much superior to the angels as the name he has inherited is superior to theirs.(N)

The Son Superior to Angels

For to which of the angels did God ever say,

“You are my Son;
    today I have become your Father”[a]?(O)

Or again,

“I will be his Father,
    and he will be my Son”[b]?(P)

And again, when God brings his firstborn(Q) into the world,(R) he says,

“Let all God’s angels worship him.”[c](S)

In speaking of the angels he says,

“He makes his angels spirits,
    and his servants flames of fire.”[d](T)

But about the Son he says,

“Your throne, O God, will last for ever and ever;(U)
    a scepter of justice will be the scepter of your kingdom.
You have loved righteousness and hated wickedness;
    therefore God, your God, has set you above your companions(V)
    by anointing you with the oil(W) of joy.”[e](X)

10 He also says,

“In the beginning, Lord, you laid the foundations of the earth,
    and the heavens are the work of your hands.(Y)
11 They will perish, but you remain;
    they will all wear out like a garment.(Z)
12 You will roll them up like a robe;
    like a garment they will be changed.
But you remain the same,(AA)
    and your years will never end.”[f](AB)

13 To which of the angels did God ever say,

“Sit at my right hand(AC)
    until I make your enemies
    a footstool(AD) for your feet”[g]?(AE)

14 Are not all angels ministering spirits(AF) sent to serve those who will inherit(AG) salvation?(AH)

Footnotes

  1. Hebrews 1:5 Psalm 2:7
  2. Hebrews 1:5 2 Samuel 7:14; 1 Chron. 17:13
  3. Hebrews 1:6 Deut. 32:43 (see Dead Sea Scrolls and Septuagint)
  4. Hebrews 1:7 Psalm 104:4
  5. Hebrews 1:9 Psalm 45:6,7
  6. Hebrews 1:12 Psalm 102:25-27
  7. Hebrews 1:13 Psalm 110:1