Add parallel Print Page Options

Òfin òdodo àti àánú

23 (A)“Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀: Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.

“Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn. (B)Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.

“Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un. Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.

“Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo. (C)Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.

(D)“Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.

(E)“Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.

Òfin Ọjọ́ Ìsinmi

10 (F)“Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀. 11 Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.

12 (G)“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.

13 “Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.

Àjọ̀dún Mẹ́ta Nínú Ọdún

14 (H)“Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.

15 “Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.

“Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.

16 “Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ.

“Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.

17 “Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.

18 (I)“Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà.

“Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.

19 (J)“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ.

“Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.

Angẹli Olúwa ni yóò pèsè ọ̀nà sílẹ̀

20 “Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún. 21 Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀. 22 Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín. 23 Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò. 24 Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú. 25 Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ. 26 Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.

27 “Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ. 28 Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ. 29 Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ. 30 Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.

31 “Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun pupa títí dé Òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate: Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ. 32 Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn. 33 Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”

Laws of Justice and Mercy

23 “Do not spread false reports.(A) Do not help a guilty person by being a malicious witness.(B)

“Do not follow the crowd in doing wrong. When you give testimony in a lawsuit, do not pervert justice(C) by siding with the crowd,(D) and do not show favoritism(E) to a poor person in a lawsuit.

“If you come across your enemy’s(F) ox or donkey wandering off, be sure to return it.(G) If you see the donkey(H) of someone who hates you fallen down under its load, do not leave it there; be sure you help them with it.

“Do not deny justice(I) to your poor people in their lawsuits. Have nothing to do with a false charge(J) and do not put an innocent(K) or honest person to death,(L) for I will not acquit the guilty.(M)

“Do not accept a bribe,(N) for a bribe blinds those who see and twists the words of the innocent.

“Do not oppress a foreigner;(O) you yourselves know how it feels to be foreigners, because you were foreigners in Egypt.

Sabbath Laws

10 “For six years you are to sow your fields and harvest the crops, 11 but during the seventh year let the land lie unplowed and unused.(P) Then the poor among your people may get food from it, and the wild animals may eat what is left. Do the same with your vineyard and your olive grove.

12 “Six days do your work,(Q) but on the seventh day do not work, so that your ox and your donkey may rest, and so that the slave born in your household and the foreigner living among you may be refreshed.(R)

13 “Be careful(S) to do everything I have said to you. Do not invoke the names of other gods;(T) do not let them be heard on your lips.(U)

The Three Annual Festivals

14 “Three times(V) a year you are to celebrate a festival to me.

15 “Celebrate the Festival of Unleavened Bread;(W) for seven days eat bread made without yeast, as I commanded you. Do this at the appointed time in the month of Aviv,(X) for in that month you came out of Egypt.

“No one is to appear before me empty-handed.(Y)

16 “Celebrate the Festival of Harvest(Z) with the firstfruits(AA) of the crops you sow in your field.

“Celebrate the Festival of Ingathering(AB) at the end of the year, when you gather in your crops from the field.(AC)

17 “Three times(AD) a year all the men are to appear before the Sovereign Lord.

18 “Do not offer the blood of a sacrifice to me along with anything containing yeast.(AE)

“The fat of my festival offerings must not be kept until morning.(AF)

19 “Bring the best of the firstfruits(AG) of your soil to the house of the Lord your God.

“Do not cook a young goat in its mother’s milk.(AH)

God’s Angel to Prepare the Way

20 “See, I am sending an angel(AI) ahead of you to guard you along the way and to bring you to the place I have prepared.(AJ) 21 Pay attention to him and listen(AK) to what he says. Do not rebel against him; he will not forgive(AL) your rebellion,(AM) since my Name(AN) is in him. 22 If you listen carefully to what he says and do(AO) all that I say, I will be an enemy(AP) to your enemies and will oppose those who oppose you. 23 My angel will go ahead of you and bring you into the land of the Amorites, Hittites, Perizzites, Canaanites, Hivites and Jebusites,(AQ) and I will wipe them out. 24 Do not bow down before their gods or worship(AR) them or follow their practices.(AS) You must demolish(AT) them and break their sacred stones(AU) to pieces. 25 Worship the Lord your God,(AV) and his blessing(AW) will be on your food and water. I will take away sickness(AX) from among you, 26 and none will miscarry or be barren(AY) in your land. I will give you a full life span.(AZ)

27 “I will send my terror(BA) ahead of you and throw into confusion(BB) every nation you encounter. I will make all your enemies turn their backs and run.(BC) 28 I will send the hornet(BD) ahead of you to drive the Hivites, Canaanites and Hittites(BE) out of your way. 29 But I will not drive them out in a single year, because the land would become desolate and the wild animals(BF) too numerous for you. 30 Little by little I will drive them out before you, until you have increased enough to take possession(BG) of the land.

31 “I will establish your borders from the Red Sea[a] to the Mediterranean Sea,[b] and from the desert to the Euphrates River.(BH) I will give into your hands the people who live in the land, and you will drive them out(BI) before you. 32 Do not make a covenant(BJ) with them or with their gods. 33 Do not let them live in your land or they will cause you to sin against me, because the worship of their gods will certainly be a snare(BK) to you.”

Footnotes

  1. Exodus 23:31 Or the Sea of Reeds
  2. Exodus 23:31 Hebrew to the Sea of the Philistines