Marku 1:35
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Jesu ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ láti gbàdúrà
35 (A)Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà.
Read full chapter
Luku 3:21
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìtẹ̀bọmi àti ìtàn ìdílé Jesu
21 (A)(B) Nígbà tí a ṣe ìtẹ̀bọmi àwọn ènìyàn gbogbo tán, ó sì ṣe, a bamitiisi Jesu pẹ̀lú, bí ó ti ń gbàdúrà, ọ̀run ṣí sílẹ̀,
Read full chapter
Luku 5:16
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
16 (A)Ṣùgbọ́n lọ́pọ̀ ìgbà ni Jesu a máa yẹra kúrò si ibi ìdákẹ́rọ́rọ́, òun á sì máa dá wà láti gbàdúrà.
Read full chapter
Luku 6:12
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àwọn aposteli méjìlá
12 (A)(B) Ni ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Jesu lọ sí orí òkè láti gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.
Read full chapter
Luku 9:18
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Peteru pe Jesu ní ọmọ Ọlọ́run
18 (A)(B) Ó sì ṣe, nígbà tí ó ku òun nìkan ó gbàdúrà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀: ó sì bi wọ́n pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi mí pè?”
Read full chapter
Luku 9:28
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìràpadà
28 (A)(B) Ó sì ṣe bí ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́jọ lẹ́yìn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó mú Peteru àti Johanu àti Jakọbu, ó gun orí òkè lọ láti lọ gbàdúrà.
Read full chapter
Luku 5:33
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
A béèrè nípa àwẹ̀ lọ́wọ́ Jesu
33 (A)(B) Wọ́n wí fún pé “Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu a máa gbààwẹ̀, wọn a sì máa gbàdúrà, bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú sì ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn Farisi ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ a máa jẹ, wọn a sì máa mu pẹ̀lú.”
Read full chapter
Luku 7:18
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Jesu àti Johanu onítẹ̀bọmi
18 (A)Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu sì sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún un.
Read full chapterCopyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.